Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 34:7-23 BIBELI MIMỌ (BM)

7. “Ta ló dàbí Jobu,tí ń kẹ́gàn Ọlọrun nígbà gbogbo,

8. tí ó ń bá àwọn aṣebi kẹ́gbẹ́,tí ó sì ń bá àwọn eniyan burúkú rìn?

9. Nítorí ó ń sọ pé, ‘Kò sí èrè kankan,ninu ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun.’

10. “Nítorí náà ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin olóye,Ọlọrun kì í ṣe ibi,Olodumare kì í ṣe ohun tí kò tọ́.

11. Nítorí a máa san ẹ̀san fún eniyan gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ati gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ̀.

12. Nítòótọ́, Ọlọrun kì í ṣe ibi,bẹ́ẹ̀ ni Olodumare kì í dájọ́ èké.

13. Ta ló fi í ṣe alákòóso ayé,ta ló sì fi jẹ olórí gbogbo ayé?

14. Bí Ọlọrun bá gba ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,tí ó sì gba èémí rẹ̀ pada sọ́dọ̀,

15. gbogbo eniyan ni yóo ṣègbé,tí wọn yóo sì pada di erùpẹ̀.

16. “Bí ẹ bá ní òye, ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ.

17. Ǹjẹ́ ẹni tí ó kórìíra ìdájọ́ ẹ̀tọ́ lè jẹ́ olórí?Àbí ẹ lè dá olódodo ati alágbára lẹ́bi?

18. Ẹni tí ó tó pe ọba ní eniyan lásán,tí ó tó pe ìjòyè ní ẹni ibi;

19. ẹni tí kì í ṣe ojuṣaaju fún àwọn ìjòyè,tí kì í sì í ka ọlọ́rọ̀ sí ju talaka lọ,nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn.

20. Wọn á kú ikú òjijì, ní ọ̀gànjọ́ òru;á mi gbogbo eniyan jìgìjìgì, wọn a sì kú.Ikú á mú àwọn alágbára lọ láì jẹ́ pé eniyan fi ọwọ́ kàn wọ́n.

21. Nítorí pé ojú rẹ̀ tó gbogbo ọ̀nà tí eniyan ń tọ̀,ó sì rí gbogbo ìrìn ẹsẹ̀ wọn.

22. Kò sí ibi òkùnkùn biribiri kankan,tí àwọn eniyan burúkú lè fi ara pamọ́ sí.

23. Nítorí Ọlọrun kò nílò láti yan àkókò kan fún ẹnikẹ́ni,láti wá siwaju rẹ̀ fún ìdájọ́.

Ka pipe ipin Jobu 34