Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 14:1-9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. “Ẹnikẹ́ni tí obinrin bá bí, ọlọ́jọ́ kúkúrú ni,ó sì kún fún ìpọ́njú.

2. Yóo kọ́ yọ bí òdòdó, lẹ́yìn náà yóo sì rẹ̀ dànù.Yóo kọjá lọ bí òjìji, kò sì ní sí mọ́.

3. Ṣé irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni o dojú kọ,tí ò ń bá ṣe ẹjọ́?

4. Ta ló lè mú ohun mímọ́ jádeláti inú ohun tí kò mọ́?Kò sí ẹni náà.

5. Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá ọjọ́ fún un,tí o mọ iye oṣù rẹ̀,tí o sì ti pa ààlà tí kò lè rékọjá.

6. Mú ojú rẹ kúrò lára rẹ̀, kí ó lè sinmi,kí ó sì lè gbádùn ọjọ́ ayé rẹ̀ bí alágbàṣe.

7. “Nítorí pé ìrètí ń bẹ fún igi tí wọn gé,yóo tún pada rúwé,ẹ̀ka rẹ̀ kò sì ní ṣe aláìsọ.

8. Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ògbólógbòó ninu ilẹ̀,tí kùkùté rẹ̀ sì kú,

9. bí ó bá ti gbóòórùn omi, yóo sọ,yóo sì yọ ẹ̀ka bí ọ̀dọ́ irúgbìn.

Ka pipe ipin Jobu 14