Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 50:34-40 BIBELI MIMỌ (BM)

34. Ṣugbọn alágbára ni Olùràpadà wọn, OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ rẹ̀. Dájúdájú, yóo jà fún wọn, kí ó lè fún ayé ní ìsinmi, ṣugbọn kí ìdààmú lè bá àwọn ará Babiloni.”

35. OLUWA ní,“Idà ni yóo pa àwọn ará Kalidea,idà ni yóo pa àwọn ará Babiloni,ati àwọn ìjòyè wọn,ati àwọn amòye wọn!

36. Idà ni yóo pa àwọn awoṣẹ́ wọn,kí wọ́n lè di òpè!Idà ni yóo pa àwọn ọmọ ogun wọn,kí wọ́n lè parẹ́!

37. Idà ni yóo pa àwọn ẹṣin wọn,ati àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn,idà ni yóo pa gbogbo àwọn àjèjì ọmọ ogun tí wọ́n wà láàrin wọn,Kí wọ́n lè di obinrin!Idà ni yóo fọ́ àwọn ilé ìṣúra wọn,kí wọ́n lè di ìkógun!

38. Ọ̀dá yóo dá ní ilẹ̀ wọn,kí àwọn odò wọn lè gbẹ!Nítorí pé ilẹ̀ tí ó kún fún ère ni,wọ́n sì kúndùn ìbọ̀rìṣà.

39. “Nítorí náà àwọn ẹranko ìgbẹ́ ati ìkookò ni yóo máa gbé inú Babiloni, ẹyẹ ògòǹgò yóo máa gbé inú rẹ̀. Kò ní sí eniyan níbẹ̀, ẹnikẹ́ni kò ní gbé inú rẹ̀ mọ́ títí lae.

40. Yóo dàbí ìgbà tí Ọlọrun pa Sodomu ati Gomora run, pẹlu àwọn ìlú tí ó yí wọn ká; nítorí náà ẹnikẹ́ni kò ní gbé ibẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni eniyan kò ní máa dé sibẹ.

Ka pipe ipin Jeremaya 50