Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 49:6-9 BIBELI MIMỌ (BM)

6. “Ṣugbọn lẹ́yìn náà, n óo dá ire àwọn ará Amoni pada.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

7. Ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ nípa Edomu nìyí: Ó ní,“Ṣé kò sí ọgbọ́n ní Temani mọ́ ni?Àbí àwọn amòye kò ní ìmọ̀ràn lẹ́nu mọ́?Ṣé ọgbọ́n ti rá mọ́ wọn ninu ni?

8. Ẹ̀yin ará Dedani, ẹ pada kíá, ẹ máa sálọ.Ẹ wọ inú ihò lọ, kí ẹ lọ máa gbébẹ̀!Nítorí pé ní ìgbà tí mo bá jẹ ìran Esau níyà, n óo mú kí ibi dé bá wọn.

9. Bí àwọn tí ń kórè èso àjàrà bá bẹ̀rẹ̀ sí kórè,ṣebí wọn a máa fi èso díẹ̀ díẹ̀ sílẹ̀?Bí àwọn olè bá wọlé lóru,ṣebí ìba ohun tí ó bá wù wọ́n ni wọn yóo kó?

Ka pipe ipin Jeremaya 49