Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 49:4-10 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Kí ló dé tí ò ń fọ́nnu nípa agbára rẹ,ipá rẹ ti pin, ìwọ olóríkunkun ọmọbinrinìwọ tí o gbójú lé ọrọ̀ rẹ,tí ò ń wí pé, ‘Ta ló lè dojú kọ mí?’

5. Wò ó! N óo kó ìpayà bá ọ,láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí wọ́n yí ọ ká;èmi OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.Gbogbo yín ni yóo fọ́nká,tí olukuluku yóo sì yà sí ọ̀nà tirẹ̀,kò sì ní sí ẹni tí yóo kó àwọn tí ń sá fún ogun jọ.

6. “Ṣugbọn lẹ́yìn náà, n óo dá ire àwọn ará Amoni pada.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

7. Ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ nípa Edomu nìyí: Ó ní,“Ṣé kò sí ọgbọ́n ní Temani mọ́ ni?Àbí àwọn amòye kò ní ìmọ̀ràn lẹ́nu mọ́?Ṣé ọgbọ́n ti rá mọ́ wọn ninu ni?

8. Ẹ̀yin ará Dedani, ẹ pada kíá, ẹ máa sálọ.Ẹ wọ inú ihò lọ, kí ẹ lọ máa gbébẹ̀!Nítorí pé ní ìgbà tí mo bá jẹ ìran Esau níyà, n óo mú kí ibi dé bá wọn.

9. Bí àwọn tí ń kórè èso àjàrà bá bẹ̀rẹ̀ sí kórè,ṣebí wọn a máa fi èso díẹ̀ díẹ̀ sílẹ̀?Bí àwọn olè bá wọlé lóru,ṣebí ìba ohun tí ó bá wù wọ́n ni wọn yóo kó?

10. Ṣugbọn mo ti tú àwọn ọmọ Esau sí ìhòòhò,Mo ti sọ ibi tí wọn ń sápamọ́ sí di gbangba,wọn kò sì rí ibi sápamọ́ sí mọ́.Àwọn ọmọ wọn ti parun,pẹlu àwọn arakunrin wọn ati àwọn aládùúgbò wọn;àwọn pàápàá sì ti di àwátì.

Ka pipe ipin Jeremaya 49