Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 3:18-25 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Nígbà tí àkókò bá tó, àwọn ará ilé Juda yóo tọ àwọn ará ilé Israẹli lọ, wọn yóo sì jọ pada láti ilẹ̀ ìhà àríwá, wọn yóo wá sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín tí wọ́n jogún.”

19. OLUWA ní,“Israẹli, mo fẹ́ fi ọ́ ṣe ọ̀kan ninu àwọn ọmọ mi,tí n óo sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó dára,kí n sì fún ọ ní ogún tí ó dára jù,láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè yòókù.Mo sì rò pé o óo máa pè mí ní baba rẹ,ati pé o kò ní pada kúrò lẹ́yìn mi.

20. Dájúdájú bí obinrin alaiṣootọ tíí fi ọkọ rẹ̀ sílẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni o ti ṣe alaiṣootọ sí mi, ìwọ Israẹli.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

21. A gbọ́ ohùn kan lórí àwọn òkè gíga,ẹkún ati ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọkunrin Israẹli ni.Nítorí wọ́n ti yapa kúrò lójú ọ̀nà wọn;wọ́n ti gbàgbé OLUWA Ọlọrun wọn.

22. Ẹ yipada, ẹ̀yin alaiṣootọ ọmọ,n óo mú aiṣootọ yín kúrò.“Wò wá! A wá sọ́dọ̀ rẹ,nítorí ìwọ ni OLUWA Ọlọrun wa.

23. Nítòótọ́, ẹ̀tàn ni àwọn òkè,ati gbogbo ohun tí wọn ń lọ ṣe níbẹ̀;dájúdájú lọ́dọ̀ OLUWA Ọlọrun wa ni ìgbàlà Israẹli wà.

24. Ṣugbọn láti ìgbà èwe wa ni ohun ìtìjú yìíti pa gbogbo ohun tí àwọn baba ńlá wa ṣiṣẹ́ fún run:ẹran ọ̀sìn wọn, ati agbo mààlúù wọn,àwọn ọmọ wọn lọkunrin ati lobinrin.

25. Ẹ jẹ́ kí á dojúbolẹ̀ kí ìtìjú wa sì bò wá,nítorí pé a ti ṣẹ̀ sí OLUWA Ọlọrun wa;àtàwa, àtàwọn baba ńlá wa,a kò gbọ́ ti OLUWA Ọlọrun wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní.”

Ka pipe ipin Jeremaya 3