Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 3:10-13 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Sibẹsibẹ, lẹ́yìn gbogbo èyí, Juda arabinrin rẹ̀, ọ̀dàlẹ̀, kò fi tọkàntọkàn pada tọ̀ mí wá. Kàkà bẹ́ẹ̀, ojú ayé ni wọ́n ń ṣe. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

11. Lẹ́yìn náà OLUWA sọ fún mi pé, “Israẹli jẹ̀bi, aiṣootọ, ṣugbọn kò tíì tó ti Juda, ọ̀dàlẹ̀.

12. Lọ kéde ọ̀rọ̀ yìí sí ìhà àríwá, kí o wí pé:‘Yipada ìwọ Israẹli alaiṣootọ.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.N kò ní bínú sí ọ, nítorí aláàánú ni mí.N kò ní máa bínú lọ títí lae.

13. Ṣá ti gbà pé o jẹ̀bi,ati pé o ti ṣọ̀tẹ̀ sí èmi OLUWA Ọlọrun rẹ.O ti fi ògo rẹ wọ́lẹ̀ fún àwọn àjèjì oriṣa,lábẹ́ gbogbo igi tútù;o kò sì gbọ́ràn sí mi lẹ́nu.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.’

Ka pipe ipin Jeremaya 3