Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 3:1-2 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA ní, “Ṣé bí ọkọ bá kọ iyawo rẹ̀ sílẹ̀,tí iyawo náà sì kó jáde nílé ọkọ,tí ó lọ fẹ́ ẹlòmíràn,ṣé ọkọ rẹ̀ àkọ́kọ́ lè tún lọ gbà á pada?Ṣé ilẹ̀ náà kò ní di ìbàjẹ́?Lẹ́yìn tí ẹ ti ṣe àgbèrè pẹlu ọpọlọpọ olólùfẹ́;ẹ wá fẹ́ pada sọ́dọ̀ mi?

2. Ẹ gbójú sókè kí ẹ wo gbogbo òkè yíká,ibo ni ẹ kò tíì ṣe àgbèrè dé?Ẹ̀ ń dúró de olólùfẹ́ lẹ́bàá ọ̀nà,bí àwọn obinrin Arabia ninu aṣálẹ̀.Ẹ ti fi ìṣekúṣe yín ba ilẹ̀ náà jẹ́.

Ka pipe ipin Jeremaya 3