Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 17:3-13 BIBELI MIMỌ (BM)

3. ati lórí àwọn òkè ninu pápá. N óo sọ gbogbo ọrọ̀ yín ati gbogbo ohun ìṣúra yín di ìkógun fún àwọn ọ̀tá yín; n óo fi gbẹ̀san ẹ̀ṣẹ̀ yín ní gbogbo ilẹ̀ yín.

4. Ìwà yín yóo mú kí ilẹ̀ tí mo fun yín bọ́ lọ́wọ́ yín; n óo sí sọ yín di ẹrú àwọn ọ̀tá yín ní ilẹ̀ tí ẹ kò mọ̀rí. Ẹ ti mú kí ibinu mi máa jó bí iná, kò sì ní kú títí lae.”

5. OLUWA ní,“Ègún ni fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé eniyan,tí ó fi ẹlẹ́ran ara ṣe agbára rẹ̀;tí ọkàn rẹ̀ yipada kúrò lọ́dọ̀ èmi OLUWA.

6. Ó dàbí igbó ṣúúrú ninu aṣálẹ̀,nǹkan rere kan kò lè ṣẹlẹ̀ sí i.Ninu ilẹ̀ gbígbẹ, ninu aṣálẹ̀ ni ó wà,ninu ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò lè gbé.

7. “Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé OLUWA,tí ó fi OLUWA ṣe àgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.

8. Yóo dàbí igi tí a gbìn sí ipa odò,tí ó ta gbòǹgbò kan ẹ̀bá odò.Ẹ̀rù kò ní bà á nígbà tí ẹ̀ẹ̀rùn bá dé,nítorí pé ewé rẹ̀ yóo máa tutù minimini.Kò ní páyà lákòókò ọ̀gbẹlẹ̀,nígbà gbogbo ni yóo sì máa so.

9. “Ọkàn eniyan kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ,ìwà ìbàjẹ́ sì kún inú rẹ̀;ta ni ó lè mọ èrò ọkàn eniyan?

10. Èmi OLUWA ni èmi máa ń wádìí èrò eniyan,tí èmi sì máa ń yẹ ọkàn eniyan wò,láti san án fún olukuluku gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀,ati gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

11. Bí àparò tíí pa ẹyin ẹlẹ́yinbẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó fi èrú kó ọrọ̀ jọ.Ọrọ̀ yóo lọ mọ́ ọn lọ́wọ́ lọ́sàn-án gangan,nígbẹ̀yìn yóo di òmùgọ̀.

12. Ìtẹ́ ògo tí a tẹ́ sí ibi gíga láti ìbẹ̀rẹ̀ ni ibi mímọ́ wa.

13. OLUWA, ìwọ ni Israẹli gbójú lé,ojú yóo ti gbogbo àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀.A óo kọ orúkọ àwọn tí wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀ sórí ilẹ̀,yóo sì parẹ́,nítorí pé wọ́n ti kọ OLUWA, orísun omi ìyè, sílẹ̀.

Ka pipe ipin Jeremaya 17