Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 13:17-27 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Ṣugbọn bí ẹ kò bá ní gbọ́,ọkàn mi yóo sọkún níkọ̀kọ̀ nítorí ìgbéraga yín.N óo sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn,omi yóo sì máa dà lójú mi,nítorí a ti kó agbo OLUWA ní ìgbèkùn.

18. Wí fún ọba ati ìyá ọba pé,“Ẹ sọ̀kalẹ̀ lórí ìtẹ́ yín,nítorí adé yín tí ó lẹ́wà ti ṣí bọ́ sílẹ̀ lórí yín.”

19. Wọ́n ti sé ìlẹ̀kùn odi àwọn ìlú ilẹ̀ Nẹgẹbukò sì sí ẹni tí yóo ṣí wọn.A ti kó gbogbo Juda lọ sí ìgbèkùn,gbogbo wọn pátá ni a ti kó lọ.

20. Ẹ gbé ojú sókè,kí ẹ wo àwọn tí ń bọ̀ láti ìhà àríwá.Àwọn agbo ẹran tí a fun yín dà,àwọn ẹran ọ̀sìn yín tí ó lẹ́wà àwọn dà?

21. Kí ni ẹ óo máa wí nígbà tí OLUWA bá mú àwọn tí ẹ fi ṣe ọ̀rẹ́,tí ó fi wọ́n jọba le yín lórí?Ǹjẹ́ ìnira kò ní ba yín, bí ìrora obinrin tí ń rọbí?

22. Bí ẹ bá wí lọ́kàn yín pé,“Kí ló dé tí irú èyí fi dé bá wa?”Ẹ̀ṣẹ̀ yín ni ó pọ̀, ni a fi ká aṣọ ní ìdí yín,tí a sì jẹ yín níyà.

23. Ṣé ó ṣeéṣe kí ará Kuṣi yí àwọ̀ ara rẹ̀ pada?Àbí kí àmọ̀tẹ́kùn fọ tóótòòtóó ara rẹ̀ dànù?Bí ó bá ṣeéṣe, á jẹ́ wí pé ẹ̀yin náà lè hùwà rere;ẹ̀yin tí ibi ṣíṣe ti mọ́ lára.

24. N óo fọn yín ká bí ìyàngbòtí afẹ́fẹ́ láti inú aṣálẹ̀ ń fẹ́ kiri.

25. Èyí ni ìpín yín,ìpín tí mo ti yàn fun yín,nítorí pé ẹ ti gbàgbé èmi OLUWA, ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ọlọrun èké.

26. Èmi gan-an ni n óo ká aṣọ lára yín,n óo sì fi bò yín lójú, kí ayé lè rí ìhòòhò yín.

27. Mo ti rí ìwà ìbàjẹ́ yín,gbogbo ìwà àgbèrè yín, bí ẹ tí ń yan ká bí akọ ẹṣin,ati ìwà ìṣekúṣe yín ní orí àwọn òkè ninu pápá.Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu, ẹ gbé!Yóo ti pẹ́ tó kí á tó wẹ̀ yín mọ́?

Ka pipe ipin Jeremaya 13