Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 10:11-21 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Wí fún wọn pé àwọn ọlọrun tí kì í ṣe àwọn ni wọ́n dá ọ̀run ati ayé yóo parun láyé ati lábẹ́ ọ̀run.

12. Òun ni ó fi agbára rẹ̀ dá ayé,tí ó fi ọgbọ́n fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀,tí ó sì fi òye rẹ̀ ta ojú ọ̀run bí aṣọ.

13. Bí ó bá fọhùn, omi á máa rọ́kẹ̀kẹ̀ lójú ọ̀run,ó mú kí ìkùukùu gbéra láti òpin ayé,òun ni ó dá mànàmáná fún òjò,tí ó sì mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.

14. Òmùgọ̀ ni gbogbo eniyan jẹ́, wọn kò sì ní ìmọ̀;gbogbo àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà ni àwọn oriṣa wọn dójútì,nítorí pé irọ́ ló wà nídìí àwọn ère wọn;kò sí èémí ninu wọn.

15. Asán ni wọ́n, ohun ìṣìnà sì ni wọ́n;ní àkókò ìjẹníyà wọn, wọn yóo parun ni.

16. Ìpín Jakọbu kò rí bí àwọn wọnyi,nítorí òun ló dá ohun gbogbo,Israẹli sì ni ẹ̀yà tí ó yàn, gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀;OLUWA àwọn ọmọ ogun ni orúkọ rẹ̀.

17. Ẹ gbé ẹrù yín nílẹ̀,ẹ̀yin tí ọ̀tá dótì wọnyi!

18. Nítorí OLUWA wí pé,“Mo ṣetán wàyí, tí n óo sọ àwọn tí wọn ń gbé ilẹ̀ yìí nù bí òkò.N óo mú kí ìpọ́njú dé bá wọn,kí wọ́n lè mọ̀ pé nǹkan ṣe àwọn.”

19. Mo gbé, nítorí mo fara gbọgbẹ́!Ọgbẹ́ náà sì pọ̀.Ṣugbọn mo sọ fún ara mi pé,“Ìyà gan-an ni èyí jẹ́ fún mi,mo sì gbọdọ̀ fara dà á.”

20. Àgọ́ mi ti wó, gbogbo okùn rẹ̀ sì ti já.Àwọn ọmọ mi ti fi mí sílẹ̀, wọn kò sì sí mọ́.Kò sí ẹni tí yóo máa bá mi pa àgọ́ mọ́,bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóo máa bá mi ta aṣọ àgọ́ mi.

21. Nítorí pé òmùgọ̀ ni àwọn olùṣọ́-aguntan,wọn kò sì ṣe ìwádìí lọ́dọ̀ OLUWA,nítorí náà wọn kò ṣe àṣeyọrí,tí gbogbo agbo wọn sì fi túká.

Ka pipe ipin Jeremaya 10