Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 1:7-12 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ṣugbọn OLUWA dá mi lóhùn, ó ní,“Má pe ara rẹ ní ọmọde,nítorí pé gbogbo ẹni tí mo bá rán ọ sí ni o gbọdọ̀ tọ̀ lọ.Gbogbo ohun tí mo bá pa láṣẹ fún ọ ni o gbọdọ̀ sọ.

8. Má bẹ̀rù wọn,nítorí mo wà pẹlu rẹ, n óo sì gbà ọ́.”

9. OLUWA bá na ọwọ́, ó fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé,“Wò ó, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ọ lẹ́nu.

10. Mo ti fi ọ́ ṣe orí fún àwọn orílẹ̀-èdè ati ìjọba lónìí,láti fà wọ́n tu ati láti bì wọ́n lulẹ̀,láti pa wọ́n run ati láti bì wọ́n ṣubú,láti tún wọn kọ́ ati láti gbé wọn ró.”

11. OLUWA bi mí pé, “Jeremaya, kí ni o rí yìí?”Mo dáhùn, pé, “Ọ̀pá igi Alimọndi ni.”

12. OLUWA bá wí fún mi pé, “Òtítọ́ ni ohun tí o rí, nítorí mò ń sọ ọ̀rọ̀ tí mo sọ, n óo sì mú un ṣẹ.”

Ka pipe ipin Jeremaya 1