Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 1:1-10 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọ̀rọ̀ Jeremaya, ọmọ Hilikaya, ọ̀kan ninu àwọn alufaa tí ó wà ní Anatoti, ní ilẹ̀ Bẹnjamini nìyí.

2. Nígbà ayé Josaya, ọmọ Amoni, ọba Juda, ní ọdún kẹtala tí Josaya gun orí oyè ni OLUWA bá Jeremaya sọ̀rọ̀.

3. Ó sì tún gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA ní ìgbà ayé Jehoiakimu, ọmọ Josaya, ọba Juda títí di òpin ọdún kọkanla tí Sedekaya ọmọ Josaya jọba ní ilẹ̀ Juda, títí tí ogun fi kó Jerusalẹmu ní oṣù karun-un ọdún náà.

4. OLUWA sọ fún mi pé,

5. “Kí n tó dá ọ sinu ìyá rẹ ni mo ti mọ̀ ọ́,kí wọ́n sì tó bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀,mo yàn ọ́ ní wolii fún àwọn orílẹ̀-èdè.”

6. Mo bá dáhùn pé,“Háà! OLUWA Ọlọrun!Wò ó! N kò mọ ọ̀rọ̀ sọ, nítorí pé ọmọde ni mí.”

7. Ṣugbọn OLUWA dá mi lóhùn, ó ní,“Má pe ara rẹ ní ọmọde,nítorí pé gbogbo ẹni tí mo bá rán ọ sí ni o gbọdọ̀ tọ̀ lọ.Gbogbo ohun tí mo bá pa láṣẹ fún ọ ni o gbọdọ̀ sọ.

8. Má bẹ̀rù wọn,nítorí mo wà pẹlu rẹ, n óo sì gbà ọ́.”

9. OLUWA bá na ọwọ́, ó fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé,“Wò ó, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ọ lẹ́nu.

10. Mo ti fi ọ́ ṣe orí fún àwọn orílẹ̀-èdè ati ìjọba lónìí,láti fà wọ́n tu ati láti bì wọ́n lulẹ̀,láti pa wọ́n run ati láti bì wọ́n ṣubú,láti tún wọn kọ́ ati láti gbé wọn ró.”

Ka pipe ipin Jeremaya 1