Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹnẹsisi 49:12-17 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Ojú rẹ̀ yóo pọ́n fún àmutẹ́rùn ọtí waini,eyín rẹ̀ yóo sì funfun fún àmutẹ́rùn omi wàrà.

13. “Sebuluni yóo máa gbé etí òkun,ọkọ̀ ojú omi rẹ̀ kò ní níye,Sidoni ni yóo jẹ́ ààlà rẹ̀.

14. “Isakari dàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó lágbáratí ó dùbúlẹ̀ láàrin gàárì ẹrù rẹ̀.

15. Ṣugbọn nígbà tí ó rí i pé ibi ìsinmi dáraati pé ilẹ̀ náà dára,ó tẹ́ ẹ̀yìn sílẹ̀ láti ru ẹrù,ó sì di ẹni tí wọn ń mú sìn bí ẹrú.

16. Dani ni yóo máa ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan rẹ̀,gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan ninu àwọn ẹ̀yà Israẹli.

17. Dani yóo dàbí ejò lójú ọ̀nà,ati bíi paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,tí ń bu ẹṣin ní gìgísẹ̀ jẹ,kí ẹni tí ó gùn ún lè ṣubú sẹ́yìn.

Ka pipe ipin Jẹnẹsisi 49