Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 31:9-23 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Má dákẹ́, kí o ṣe ìdájọ́ òdodo,bá talaka ati aláìní gba ẹ̀tọ́ wọn.

10. Ta ló lè rí iyawo tí ó ní ìwà rere fẹ́?Ó ṣọ̀wọ́n ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ.

11. Ọkọ rẹ̀ yóo fi tọkàntọkàn gbẹ́kẹ̀lé e,kò sì ní ṣaláì ní ohunkohun.

12. Rere ni obinrin náà máa ń ṣe fún unkò ní ṣe é níbi, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13. A máa lọ wá irun aguntan ati òwú ìhunṣọ,a sì máa fi tayọ̀tayọ̀ hun aṣọ.

14. Obinrin náà dàbí ọkọ̀ ojú omi oníṣòwò,tí ó ń mú oúnjẹ wálé láti ọ̀nà jíjìn réré.

15. Ìdájí níí tií jí láti wá oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀,ati láti yan iṣẹ́ fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀.

16. Bí ó bá rí ilẹ̀ oko, a yẹ̀ ẹ́ wò, a sì rà á,a sì fi èrè iṣẹ́ rẹ̀ gbin ọgbà àjàrà.

17. A fi agbára fún ọ̀já mọ́nú,a sì tẹpá mọ́ṣẹ́.

18. A máa mójútó ọjà tí ó ń tà,fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú lóru.

19. Ó fi ọwọ́ lé kẹ̀kẹ́ òwú,ó sì ń ran òwú.

20. Ó lawọ́ sí àwọn talaka,a sì máa ran àwọn aláìní lọ́wọ́.

21. Kì í bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nígbà òtútù,nítorí gbogbo wọn ni ó ti bá hun aṣọ tí ó móoru.

22. A máa hun aṣọ ọlọ́nà a sì fi bo ibùsùn rẹ̀,òun náà á wọ aṣọ funfun dáradára ati ti elése àlùkò.

23. Wọ́n dá ọkọ rẹ̀ mọ̀ lẹ́nu ibodè,nígbà tí ó bá jókòó pẹlu àwọn àgbààgbà ìlú.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 31