Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 31:6-18 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Fún ẹni tí ń ṣègbé lọ ní ọtí mu,fún àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ ní ọtí líle,

7. jẹ́ kí wọn mu ún, kí wọn gbàgbé òṣì wọn,kí wọn má sì ranti ìnira wọn mọ́.

8. Gba ẹjọ́ àwọn tí kò ní ẹnu ọ̀rọ̀ rò,ati ti àwọn tí a sọ di aláìní.

9. Má dákẹ́, kí o ṣe ìdájọ́ òdodo,bá talaka ati aláìní gba ẹ̀tọ́ wọn.

10. Ta ló lè rí iyawo tí ó ní ìwà rere fẹ́?Ó ṣọ̀wọ́n ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ.

11. Ọkọ rẹ̀ yóo fi tọkàntọkàn gbẹ́kẹ̀lé e,kò sì ní ṣaláì ní ohunkohun.

12. Rere ni obinrin náà máa ń ṣe fún unkò ní ṣe é níbi, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13. A máa lọ wá irun aguntan ati òwú ìhunṣọ,a sì máa fi tayọ̀tayọ̀ hun aṣọ.

14. Obinrin náà dàbí ọkọ̀ ojú omi oníṣòwò,tí ó ń mú oúnjẹ wálé láti ọ̀nà jíjìn réré.

15. Ìdájí níí tií jí láti wá oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀,ati láti yan iṣẹ́ fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀.

16. Bí ó bá rí ilẹ̀ oko, a yẹ̀ ẹ́ wò, a sì rà á,a sì fi èrè iṣẹ́ rẹ̀ gbin ọgbà àjàrà.

17. A fi agbára fún ọ̀já mọ́nú,a sì tẹpá mọ́ṣẹ́.

18. A máa mójútó ọjà tí ó ń tà,fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú lóru.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 31