Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 31:3-15 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Má ṣe lo agbára rẹ lórí obinrin,má fi ọ̀nà rẹ lé àwọn tí wọn ń pa ọba run lọ́wọ́.

4. Gbọ́, ìwọ Lemueli,ọba kò gbọdọ̀ máa mu ọtí,àwọn aláṣẹ kò sì gbọdọ̀ máa wá ọtí líle.

5. Kí wọn má baà mu ún tán, kí wọn gbàgbé òfin,kí wọn sì yí ìdájọ́ ẹni tí ojú ń pọ́n po.

6. Fún ẹni tí ń ṣègbé lọ ní ọtí mu,fún àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ ní ọtí líle,

7. jẹ́ kí wọn mu ún, kí wọn gbàgbé òṣì wọn,kí wọn má sì ranti ìnira wọn mọ́.

8. Gba ẹjọ́ àwọn tí kò ní ẹnu ọ̀rọ̀ rò,ati ti àwọn tí a sọ di aláìní.

9. Má dákẹ́, kí o ṣe ìdájọ́ òdodo,bá talaka ati aláìní gba ẹ̀tọ́ wọn.

10. Ta ló lè rí iyawo tí ó ní ìwà rere fẹ́?Ó ṣọ̀wọ́n ju ohun ọ̀ṣọ́ olówó iyebíye lọ.

11. Ọkọ rẹ̀ yóo fi tọkàntọkàn gbẹ́kẹ̀lé e,kò sì ní ṣaláì ní ohunkohun.

12. Rere ni obinrin náà máa ń ṣe fún unkò ní ṣe é níbi, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13. A máa lọ wá irun aguntan ati òwú ìhunṣọ,a sì máa fi tayọ̀tayọ̀ hun aṣọ.

14. Obinrin náà dàbí ọkọ̀ ojú omi oníṣòwò,tí ó ń mú oúnjẹ wálé láti ọ̀nà jíjìn réré.

15. Ìdájí níí tií jí láti wá oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀,ati láti yan iṣẹ́ fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 31