Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 31:16-25 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Bí ó bá rí ilẹ̀ oko, a yẹ̀ ẹ́ wò, a sì rà á,a sì fi èrè iṣẹ́ rẹ̀ gbin ọgbà àjàrà.

17. A fi agbára fún ọ̀já mọ́nú,a sì tẹpá mọ́ṣẹ́.

18. A máa mójútó ọjà tí ó ń tà,fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú lóru.

19. Ó fi ọwọ́ lé kẹ̀kẹ́ òwú,ó sì ń ran òwú.

20. Ó lawọ́ sí àwọn talaka,a sì máa ran àwọn aláìní lọ́wọ́.

21. Kì í bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nígbà òtútù,nítorí gbogbo wọn ni ó ti bá hun aṣọ tí ó móoru.

22. A máa hun aṣọ ọlọ́nà a sì fi bo ibùsùn rẹ̀,òun náà á wọ aṣọ funfun dáradára ati ti elése àlùkò.

23. Wọ́n dá ọkọ rẹ̀ mọ̀ lẹ́nu ibodè,nígbà tí ó bá jókòó pẹlu àwọn àgbààgbà ìlú.

24. A máa hun aṣọ funfun, a sì tà wọ́n,a máa ta ọ̀já ìgbànú fún àwọn oníṣòwò.

25. Agbára ati ọlá ni ó fi ń bora bí aṣọ,ó sì ní ìrètí ayọ̀ nípa ọjọ́ iwájú.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 31