Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 31:13-31 BIBELI MIMỌ (BM)

13. A máa lọ wá irun aguntan ati òwú ìhunṣọ,a sì máa fi tayọ̀tayọ̀ hun aṣọ.

14. Obinrin náà dàbí ọkọ̀ ojú omi oníṣòwò,tí ó ń mú oúnjẹ wálé láti ọ̀nà jíjìn réré.

15. Ìdájí níí tií jí láti wá oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀,ati láti yan iṣẹ́ fún àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀.

16. Bí ó bá rí ilẹ̀ oko, a yẹ̀ ẹ́ wò, a sì rà á,a sì fi èrè iṣẹ́ rẹ̀ gbin ọgbà àjàrà.

17. A fi agbára fún ọ̀já mọ́nú,a sì tẹpá mọ́ṣẹ́.

18. A máa mójútó ọjà tí ó ń tà,fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú lóru.

19. Ó fi ọwọ́ lé kẹ̀kẹ́ òwú,ó sì ń ran òwú.

20. Ó lawọ́ sí àwọn talaka,a sì máa ran àwọn aláìní lọ́wọ́.

21. Kì í bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nígbà òtútù,nítorí gbogbo wọn ni ó ti bá hun aṣọ tí ó móoru.

22. A máa hun aṣọ ọlọ́nà a sì fi bo ibùsùn rẹ̀,òun náà á wọ aṣọ funfun dáradára ati ti elése àlùkò.

23. Wọ́n dá ọkọ rẹ̀ mọ̀ lẹ́nu ibodè,nígbà tí ó bá jókòó pẹlu àwọn àgbààgbà ìlú.

24. A máa hun aṣọ funfun, a sì tà wọ́n,a máa ta ọ̀já ìgbànú fún àwọn oníṣòwò.

25. Agbára ati ọlá ni ó fi ń bora bí aṣọ,ó sì ní ìrètí ayọ̀ nípa ọjọ́ iwájú.

26. Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n ní ń jáde láti ẹnu rẹ̀,a sì máa kọ́ni ní ẹ̀kọ́ àánú.

27. A máa ṣe ìtọ́jú ìdílé rẹ̀ dáradára,kì í sì í hùwà ọ̀lẹ.

28. Àwọn ọmọ rẹ̀ a máa pè é ní ẹni ibukun,ọkọ rẹ̀ pẹlu a sì máa yìn ín pé,

29. “Ọpọlọpọ obinrin ni wọ́n ti ṣe ribiribi,ṣugbọn ìwọ ta gbogbo wọn yọ.”

30. Ẹ̀tàn ni ojú dáradára, asán sì ni ẹwà,obinrin tí ó bá bẹ̀rù OLUWA ni ó yẹ kí á yìn.

31. Fún un ninu èrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀,jẹ́ kí wọn máa yìn ín lẹ́nu ibodè nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 31