24. Ẹni tí ó ja ìyá tabi baba rẹ̀ lólè,tí ó ní, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”,ẹlẹgbẹ́ apanirun ni.
25. Olójúkòkòrò eniyan a máa dá ìjà sílẹ̀,ṣugbọn ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo ṣe rere.
26. Òmùgọ̀ ni ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀,ẹni tí ń fi ọgbọ́n rìn yóo là.
27. Ẹni tí ó ta talaka lọ́rẹ kò ní ṣe aláìní,ṣugbọn ẹni tí ó fojú pamọ́ fún wọn, yóo gba ègún.
28. Nígbà tí àwọn eniyan burúkú bá dìde,àwọn eniyan á sá pamọ́,ṣugbọn nígbà tí wọ́n bá parun, olódodo á pọ̀ sí i.