Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 22:10-23 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Lé pẹ̀gànpẹ̀gàn síta, ìjà yóo rọlẹ̀,asọ̀ ati èébú yóo sì dópin.

11. Ẹni tí ó fẹ́ ọkàn mímọ́,tí ó sì ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu yóo bá ọba ṣọ̀rẹ́.

12. Ojú OLUWA ń ṣọ́ ìmọ̀ tòótọ́,ṣugbọn a máa yí ọ̀rọ̀ àwọn alaigbagbọ po.

13. Ọ̀lẹ a máa sọ pé, “Kinniun wà níta!Yóo pa mí jẹ lójú pópó!”

14. Ẹnu alágbèrè obinrin dàbí kòtò ńlá,ẹni tí OLUWA bá ń bínú sí níí já sinu rẹ̀.

15. Ìwà agídí dì sí ọkàn ọmọde,ṣugbọn pàṣán ìbáwí níí lé e jáde.

16. Ẹni tí ó ni talaka lára kí ó lè ní ohun ìní pupọ,tabi tí ó ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ yóo pada di talaka.

17. Tẹ́tí rẹ sílẹ̀ kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n,kí o sì fi ọkàn sí ẹ̀kọ́ mi,

18. nítorí yóo dára tí o bá pa wọ́n mọ́ lọ́kàn rẹ,tí o sì ń fi wọ́n ṣe ọ̀rọ̀ sọ jáde.

19. Ìwọ ni mo sọ wọ́n di mímọ̀ fún lónìí, àní ìwọ,kí ó le jẹ́ pé OLUWA ni o gbẹ́kẹ̀lé.

20. Ṣebí mo ti kọ ọgbọ̀n àkọsílẹ̀ fún ọ lórí ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n,

21. láti fi ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì jẹ́ òtítọ́ hàn ọ́,kí o lè fi ìdáhùn pípé fún ẹni tí ó rán ọ.

22. Má ja talaka lólè, nítorí pé ó jẹ́ talaka,má sì dájọ́ èké fún ẹni tí ara ń ni.

23. Nítorí OLUWA yóo gbèjà wọn,yóo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń jẹ wọ́n níyà.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 22