Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 21:8-23 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún,ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́.

9. Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

10. Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́,àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀.

11. Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n,tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i.

12. Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú,eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun.

13. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka,òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn.

14. Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu,àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà.

15. Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn,ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi.

16. Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òyeyóo sinmi láàrin àwọn òkú.

17. Ẹni tí ó fẹ́ràn fàájì yóo di talaka,ẹni tí ó fẹ́ràn ọtí waini ati òróró kò ní lówó lọ́wọ́.

18. Eniyan burúkú ni yóo forí gba ibitíì bá dé bá olódodo.Alaiṣootọ ni yóo fara gba ìyà tí ó tọ́ sí olóòótọ́ inú.

19. Ó sàn láti máa gbé ààrin aṣálẹ̀,ju kí eniyan máa bá oníjà ati oníkanra obinrin gbé lọ.

20. Ní ilé ọlọ́gbọ́n ni à á tí ń bá nǹkan olówó iyebíye,ṣugbọn òmùgọ̀ a máa ba tirẹ̀ jẹ́.

21. Ẹni tí ń lépa òdodo ati àánúyóo rí ìyè, òdodo, ati iyì.

22. Ọlọ́gbọ́n a máa gba ìlú àwọn alágbáraa sì wó ibi ààbò tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé lulẹ̀.

23. Ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́pa ara rẹ̀ mọ́ kúrò ninu ìyọnu.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 21