Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 21:5-16 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Dájúdájú èrò ẹni tí ó ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóo yọrí sí ọ̀pọ̀,ṣugbọn ẹni tí ó bá ń kánjú jù kò ní ní ànító.

6. Fífi èké kó ìṣúra jọdàbí lílé ìkùukùu, ó sì jẹ́ tàkúté ikú.

7. Ìwà ipá àwọn ẹni ibi ni yóo gbá wọn dànù,nítorí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe òtítọ́.

8. Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún,ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́.

9. Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

10. Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́,àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀.

11. Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n,tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i.

12. Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú,eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun.

13. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka,òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn.

14. Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu,àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà.

15. Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn,ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi.

16. Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òyeyóo sinmi láàrin àwọn òkú.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 21