Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 15:4-15 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ọ̀rọ̀ tí a fi pẹ̀lẹ́ sọ dàbí igi ìyè,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn a máa bani lọ́kàn jẹ́.

5. Òmùgọ̀ ọmọ á kẹ́gàn ìtọ́sọ́nà baba rẹ̀,ṣugbọn ọmọ tí ó gbọ́ ìkìlọ̀, ọlọ́gbọ́n ni.

6. Ilé olódodo kún fún ọpọlọpọ ìṣúra,ṣugbọn kìkì ìdààmú ni àkójọ èrè eniyan burúkú.

7. Ẹnu ọlọ́gbọ́n a máa tan ìmọ̀ kálẹ̀,ṣugbọn ti òmùgọ̀ kò rí bẹ́ẹ̀.

8. Ohun ìríra ni ẹbọ eniyan burúkú lójú OLUWA,ṣugbọn adura olódodo jẹ́ ìdùnnú rẹ̀.

9. OLUWA kórìíra ìwà àwọn eniyan burúkú,ṣugbọn ó fẹ́ràn àwọn tí ń hùwà òdodo.

10. Ìbáwí pupọ ń bẹ fún ẹni tí ó yapa kúrò ní ọ̀nà rere,ẹni tí ó bá kórìíra ìbáwí yóo kú.

11. Isà òkú ati ìparun kò pamọ́ lójú OLUWA,mélòó-mélòó ni ọkàn eniyan.

12. Inú pẹ̀gànpẹ̀gàn kì í dùn sí ìbáwí,kì í bèèrè ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ọlọ́gbọ́n.

13. Inú dídùn a máa múni dárayá,ṣugbọn ìbànújẹ́ a máa mú kí ojú eniyan rẹ̀wẹ̀sì.

14. Ẹni tí ó ní òye a máa wá ìmọ̀,ṣugbọn agọ̀ ni oúnjẹ òmùgọ̀.

15. Gbogbo ọjọ́ ayé ẹni tí a ni lára kún fún ìpọ́njú,ṣugbọn ojoojumọ ni ọdún fún ẹni tí inú rẹ̀ dùn.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 15