Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Oníwàásù 3:7-14 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Àkókò fífa nǹkan ya wà, àkókò rírán nǹkan pọ̀ sì wà;àkókò dídákẹ́ wà, àkókò ọ̀rọ̀ sísọ sì wà.

8. Àkókò láti fi ìfẹ́ hàn wà àkókò láti kórìíra sì wà;àkókò ogun wà, àkókò alaafia sì wà.

9. Kí ni èrè làálàá òṣìṣẹ́?

10. Mo ti mọ ẹrù ńlá tí Ọlọrun dì ru ọmọ eniyan.

11. Ó ṣe ohun gbogbo dáradára, ní àkókò rẹ̀. Ó fi ayérayé sí ọkàn eniyan, sibẹ, ẹnikẹ́ni kò lè rídìí ohun tí Ọlọrun ṣe láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.

12. Mo mọ̀ pé kò sí ohun tí ó yẹ wọ́n ju pé kí inú wọn máa dùn, kí wọ́n sì máa ṣe rere ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn;

13. ati pé ẹ̀bùn Ọlọrun ni pé kí olukuluku jẹ, kí ó mu, kí ó sì gbádùn lẹ́yìn làálàá rẹ̀.

14. Mo mọ̀ pé gbogbo ohun tí Ọlọrun ṣe, yóo wà títí lae. Kò sí ohun tí ẹ̀dá lè fi kún un, tabi tí ẹ̀dá lè yọ kúrò níbẹ̀, Ọlọrun ni ó dá a bẹ́ẹ̀ kí eniyan lè máa bẹ̀rù rẹ̀.

Ka pipe ipin Ìwé Oníwàásù 3