Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Isikiẹli 31:7-11 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ó tóbi, ó lọ́lá ẹ̀ka rẹ̀ sì lẹ́wànítorí pé gbòǹgbò rẹ̀ wọ ilẹ̀ lọ,ó sì kan ọpọlọpọ omi nísàlẹ̀ ilẹ̀.

8. Igi kedari tí ó wà ninu ọgbà Ọlọrun kò lè farawé e.Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ka igi firi kò sì tó ẹ̀ka rẹ̀.Ẹ̀ka igi kankan kò dàbí ẹ̀ka rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò sí igikígi ninu ọgbà Ọlọrun tí ó lẹ́wà bíi rẹ̀.

9. Mo dá a ní arẹwà, pẹlu ẹ̀ka tí ó pọ̀.Gbogbo igi ọgbà Edẹni,tí ó wà ninu ọgbà Ọlọrun sì ń jowú rẹ̀.

10. “Nítorí pé ó ga sókè fíofío, góńgó orí rẹ̀ wọ inú ìkùukùu lójú ọ̀run, ọkàn rẹ̀ sì kún fún ìgbéraga nítorí gíga rẹ̀.

11. N óo fi lé ẹni tí ó lágbára jù láàrin àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, yóo sì ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà ìkà rẹ̀. Èmi OLUWA Ọlọrun ni mo sọ bẹ́ẹ̀. N óo lé e jáde.

Ka pipe ipin Isikiẹli 31