Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Isikiẹli 30:4-10 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ogun yóo jà ní Ijipti,ìrora yóo sì bá Etiopia.Nígbà tí ọpọlọpọ òkú bá sùn ní Ijipti,tí a kó ọrọ̀ rẹ̀ lọ,tí a sì wó ìpìlẹ̀ rẹ̀ lulẹ̀.

5. “ ‘Àwọn ará Etiopia, ati Puti, ati Ludi, ati gbogbo ilẹ̀ Arabia ati Libia, ati gbogbo àwọn eniyan wa tí wọ́n jọ gbìmọ̀ pọ̀, ni ogun yóo pa.’ ”

6. OLUWA ní, “Àwọn tí ń ran Ijipti lọ́wọ́ yóo ṣubú,ìgbéraga rẹ̀ yóo sì wálẹ̀;láti Migidoli títí dé Siene,wọn ó kú ikú ogun láàrin ìlú.Èmi OLUWA Ọlọrun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

7. “Ijipti óo di ahoro patapata àwọn ìlú rẹ̀ yóo wà lára àwọn ìlú tí yóo tú patapata.

8. Wọn yóo mọ̀ pé èmi ni OLUWA nígbà tí mo bá dáná sun Ijipti, tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá ṣubú.

9. “Nígbà tó bá tó àkókò, n óo rán àwọn ikọ̀ ninu ọkọ̀ ojú omi, wọn ó lọ dẹ́rù ba àwọn ará Etiopia tí wọn ń gbé láìfura. Wahala yóo dé bá àwọn ará Etiopia ní ọjọ́ ìparun Ijipti. Wò ó, ìparun náà ti dé tán.”

10. OLUWA Ọlọrun ní, “N óo ti ọwọ́ Nebukadinesari, ọba Babiloni, fi òpin sí ọrọ̀ Ijipti.

Ka pipe ipin Isikiẹli 30