Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Isikiẹli 27:20-34 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Àwọn ará Dedani náà ń bá ọ ṣòwò, wọ́n ń kó aṣọ gàárì tí wọ́n fi ń gun ẹṣin wá.

21. Àwọn ará Arabia ati àwọn olóyè Kedari ni àwọn oníbàárà rẹ pataki, wọn a máa ra ọ̀dọ́ aguntan, àgbò, ati ewúrẹ́ lọ́wọ́ rẹ.

22. Àwọn oníṣòwò Ṣeba ati ti Raama náà a máa bá ọ ra ọjà, oríṣìíríṣìí turari olóòórùn dídùn ati òkúta olówó iyebíye ati wúrà ni wọ́n fi ń ṣe pàṣípààrọ̀ ọjà lọ́wọ́ rẹ.

23. Àwọn ará Harani, Kane, Edẹni, Aṣuri ati Kilimadi ń bá ọ ṣòwò.

24. Wọ́n ń kó ojúlówó ẹ̀wù aṣọ aláwọ̀ aró wá tà fún ọ, ati aṣọ tí wọ́n ṣe iṣẹ́ ọnà sí lára, ati ẹni tí ó ní oríṣìíríṣìí àwọ̀, tí wọ́n fi ìko hun.

25. Àwọn ọkọ̀ Taṣiṣi ní ń bá ọ ru ọjà rẹ lọ ta.Ọjà kún inú rẹ,ẹrù rìn ọ́ mọ́lẹ̀ láàrin omi òkun.

26. Àwọn tí ń wà ọ́ ti tì ọ́ sí ààrin agbami òkun.Atẹ́gùn ńlá ti dà ọ́ nù láàrin agbami òkun.

27. Gbogbo ọrọ̀ rẹ, ati gbogbo ọjà olówó iyebíye rẹ,àwọn tí ń tu ọkọ̀ rẹ ati àwọn tí ń darí rẹ;àwọn tí ń fi ọ̀dà dí ihò ara ọkọ̀ rẹati àwọn tí ń bá ọ ṣòwò.Gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ ati àwọn èrò tí ó wà ninu rẹ,ni yóo rì sí ààrin gbùngbùn òkun, ní ọjọ́ ìparun rẹ.

28. Gbogbo èbúté yóo mì tìtìnígbà tí àwọn tí wọn ń tọ́ ọkọ̀ rẹ bá kígbe.

29. Gbogbo àwọn atukọ̀ ni yóo jáde kúrò ninu ọkọ̀.Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ninu ọkọ̀ati àwọn tí ń darí ọkọ̀yóo dúró ní èbúté.

30. Wọn óo gbé ohùn sókè sí ọ,wọn óo sun ẹkún kíkan kíkan.Wọn óo da erùpẹ̀ sórí wọn,wọn óo yíra mọ́lẹ̀ ninu eérú.

31. Wọn óo fá irun orí wọn nítorí rẹ,wọn óo sán aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ìdí,wọn óo sì fi ìbànújẹ́ ọkàn sọkún nítorí rẹ,inú wọn yóo sì bàjẹ́.

32. Bí wọ́n bá ti ń sọkún,wọn óo máa kọ orin arò nípa rẹ báyìí pé:‘Ìlú wo ló tíì parun bíi Tire, láàrin òkun?

33. Nígbà tí àwọn ọjà rẹ bá dé láti òkè òkun,ò ń tẹ́ ọpọlọpọ eniyan lọ́rùn.Ò ń fi ọpọlọpọ ọrọ̀ rẹ ati ọjà rẹsọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.

34. Wàyí ò, omi òkun ti fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́,o ti rì sí ìsàlẹ̀ òkun.’Gbogbo àwọn ọjà rẹati àwọn tí ń wa ọkọ̀ rẹ ti rì pẹlu rẹ.

Ka pipe ipin Isikiẹli 27