Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremaya 2:14-22 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Ìran èké ati ti ẹ̀tàn ni àwọn wolii rẹ ń rí sí ọ;wọn kò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn ọ́,kí wọ́n lè dá ire rẹ pada,ṣugbọn wọ́n ń ríran èké ati ìran ẹ̀tàn sí ọ.

15. Gbogbo àwọn tí ń rékọjá lọń pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,wọ́n ń pòṣé,wọ́n sì ń mi orí wọn sí ọ, Jerusalẹmu.Wọ́n ń sọ pé:“Ṣé ìlú yìí ni à ń pè níìlú tí ó lẹ́wà jùlọ,tí ó jẹ́ ayọ̀ gbogbo ayé?”

16. Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ọ́ ṣẹ̀sín,wọ́n ń pòṣé,wọ́n ń fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà.Wọ́n ń wí pé:“A ti pa á run!Ọjọ́ tí a tí ń retí nìyí;ọwọ́ wa ti tẹ Jerusalẹmu wàyí!A ti rí ohun tí à ń wá!”

17. OLUWA ti ṣe bí ó ti pinnu,ó ti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ,bí ó ti sọ ní ìgbà àtijọ́.Ó ti wó ọ lulẹ̀ láìṣàánú rẹ;ó ti jẹ́ kí ọ̀tá yọ̀ ọ́,ó ti fún àwọn ọ̀tá rẹ ni agbára kún agbára.

18. Ẹ kígbe sí OLUWA,ẹ̀yin ará Sioni!Ẹ jẹ́ kí omi máa dà lójú yín pòròpòrò tọ̀sán-tòru;ẹ má sinmi,ẹ má sì jẹ́ kí oorun kùn yín.

19. Ẹ dìde, ẹ kígbe lálẹ́,ní àkókò tí àwọn aṣọ́de ń bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́!Ẹ tú ẹ̀dùn ọkàn yín jáde bí omi níwájú OLUWA!Ẹ gbé ọwọ́ ẹ̀bẹ̀ sókè sí i,nítorí ẹ̀mí àwọn ọmọ yín tí ebi ń pa kú lọ ní gbogbo ìkóríta.

20. Wò ó! OLUWA,ṣe akiyesi ohun tí ń ṣẹlẹ̀!Wo àwọn tí ò ń ṣe irú èyí sí!Ṣé ó yẹ kí àwọn obinrin máa jẹ ọmọ wọn?Ọmọ ọwọ́ tí wọn ń tọ́jú!Ṣé ó yẹ kí á pa alufaa ati wolii, ní ibi mímọ́ OLUWA?

21. Àtàwọn ọ̀dọ́, àtàwọn arúgbówọ́n kú kalẹ̀ lọ lójú pópó,àtàwọn ọdọmọbinrin, àtàwọn ọdọmọkunrin mi,gbogbo wọn ni idà ti pa.Ní ọjọ́ ibinu rẹ ni o pa wọ́n,o pa wọ́n ní ìpakúpa láìṣàánú wọn.

22. O pe àwọn ọ̀tá mi jọ sí mibí ẹni peniyan síbi àjọ̀dún;kò sì sí ẹni tí ó yèní ọjọ́ ibinu rẹ, OLUWA.Ọ̀tá mi pa àwọn ọmọ mi run,àwọn tí mo tọ́, tí mo sì fẹ́ràn.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremaya 2