Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Ọba Kinni 14:24-31 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Àwọn ọkunrin tí wọ́n sọ ara wọn di aṣẹ́wó ní ojúbọ àwọn oriṣa náà sì pọ̀ ní ilẹ̀ náà. Gbogbo ohun ìríra tí àwọn orílẹ̀-èdè tí OLUWA lé jáde fún àwọn ọmọ Israẹli ń ṣe, ni àwọn náà ń ṣe.

25. Ní ọdún karun-un ìjọba Rehoboamu, Ṣiṣaki, ọba Ijipti, gbógun ti Jerusalẹmu.

26. Ó kó gbogbo ìṣúra tí ó wà ninu ilé OLUWA ati ti ààfin ọba pátá; gbogbo apata wúrà tí Solomoni ṣe ni ó kó lọ pẹlu.

27. Rehoboamu bá ṣe apata idẹ dípò wọn. Ó sì fi àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ tí ń ṣọ́ ẹnu ọ̀nà ààfin ọba ṣe alabojuto wọn.

28. Nígbàkúùgbà tí ọba bá ń lọ sinu ilé OLUWA, àwọn ẹ̀ṣọ́ á gbé apata náà tẹ̀lé e, wọn á sì dá wọn pada sinu ilé ìṣúra lọ́dọ̀ àwọn ẹ̀ṣọ́.

29. Gbogbo àwọn nǹkan yòókù tí Rehoboamu ọba ṣe ni a kọ sílẹ̀ ninu Ìwé Ìtàn Àwọn Ọba Juda.

30. Ní gbogbo ìgbà ayé Rehoboamu ati ti Jeroboamu ni àwọn mejeeji í máa gbógun ti ara wọn.

31. Rehoboamu jáde láyé, wọ́n sì sin ín sinu ibojì ọba, ní ìlú Dafidi. Naama ará Amoni ni ìyá rẹ̀. Abijamu ọmọ rẹ̀ ni ó sì gun orí oyè lẹ́yìn rẹ̀.

Ka pipe ipin Àwọn Ọba Kinni 14