Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 9:9-21 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Gbogbo eniyan ni yóo mọ̀,àwọn ará Efuraimu ati àwọn ará Samaria,àwọn tí wọn ń fọ́nnu pẹlu ìgbéraga pé:

10. Ṣé bíríkì ni wọ́n fi kọ́ àwọn ilé tí ó wó lulẹ̀?Òkúta gbígbẹ́ ni a óo fi tún wọn kọ́.Igi sikamore ni a fi kọ́ èyí tí wọ́n dà wó,ṣugbọn igi kedari dáradára ni a óo lò dípò wọn.

11. Nítorí náà OLUWA ti gbé ọ̀tá dìde sí wọn:Ó ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè sí wọn:

12. Àwọn ará Siria láti ìhà ìlà oòrùn,ati àwọn ará Filistia láti ìhà ìwọ̀ oòrùn;wọn óo gbé Israẹli mì.Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

13. Sibẹsibẹ àwọn ọmọ Israẹli kò pada sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó jẹ wọ́n níyà,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò wá OLUWA àwọn ọmọ-ogun.

14. Nítorí náà, OLUWA yóo fi ìyà jẹ Israẹli.Ní ọjọ́ kan ṣoṣo, yóo gé Israẹli lórí ati nírù.

15. Àwọn àgbààgbà ati àwọn ọlọ́lá wọn ni orí,àwọn wolii tí ń kọ́ àwọn eniyan ní ẹ̀kọ́ èké sì ni ìrù

16. Àwọn tí ń darí àwọn eniyan wọnyi ń ṣì wọ́n lọ́nà ni,àwọn tí wọn ń tọ́ sọ́nà sì ń já sinu ìparun.

17. Nítorí náà, OLUWA kò láyọ̀ lórí àwọn ọdọmọkunrin wọn,àánú àwọn aláìníbaba ati àwọn opó wọn kò sì ṣe énítorí pé aṣebi ni gbogbo wọn, wọn kò sì mọ Ọlọrun,ọ̀rọ̀ burúkú ni wọ́n sì ń fi ẹnu wọn sọ.Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

18. Ìwà burúkú wọn ń jó bí iná,tí ń jó ẹ̀gún wẹ́wẹ́ ati ẹ̀gún ọ̀gàn.Ó ń jó bíi igbó ńlá, ó sì ń yọ èéfín sókè lálá.

19. Nítorí ibinu OLUWA àwọn ọmọ ogun, ilẹ̀ náà jóná,àwọn eniyan ibẹ̀ dàbí èpò tí a dà sinu ináẹnikẹ́ni kò sì dá ẹnìkejì rẹ̀ sí.

20. Wọ́n ń já nǹkan gbà lọ́tùn-ún, wọ́n ń jẹ ẹ́,sibẹ ebi ń pa wọ́n.Wọ́n ń jẹ àjẹrun lósì,sibẹ wọn kò yó,àwọn eniyan sì ń pa ara wọn jẹ.

21. Àwọn ará Manase ń bá àwọn ará Efuraimu jà,bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Efuraimu náà ń bá àwọn ará Manase jà.Àwọn mejeeji wá dojú ìjà kọ Juda.Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò dáwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.

Ka pipe ipin Aisaya 9