Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 57:1-11 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Olódodo ń ṣègbé,kò sí ẹni tí ó fi ọkàn sí i.A mú àwọn olótìítọ́ kúrò, kò sì sí ẹni tí ó yé,pé à ń yọ olódodo kúrò ninu ìdààmú ni.

2. Àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà òtítọ́, wọn óo wà ní alaafia,wọn óo máa sinmi lórí ibùsùn wọn.

3. Ẹ̀yin ọmọ oṣó wọnyi,ẹ súnmọ́bí fún ìdájọ́,ẹ̀yin ọmọ alágbèrè ati panṣaga.

4. Ta ni ẹ̀ ń fi ṣe ẹlẹ́yà?Ta ni ẹ̀ ń ya ẹnu ní ìyàkuyà sítí ẹ yọ ṣùtì sí?Ṣebí ọmọ ẹ̀ṣẹ̀ ni yínirú ọmọ ẹ̀tàn;

5. ẹ̀yin tí ẹ kún fún ìṣekúṣe lábẹ́ igi Oaku,ati lábẹ́ gbogbo igi eléwé tútù.Ẹ̀yin tí ẹ̀ ń pa àwọn ọmọ yín láàrin àfonífojì,ati ní abẹ́ àpáta?

6. Àwọn oriṣa láàrin àwọn òkúta ọ̀bọ̀rọ́, ninu àfonífojì,àwọn ni ẹ̀ ń sìn,àwọn ni ò ń da ẹbọ ohun mímu lé lórí,àwọn ni ò ń fi nǹkan jíjẹ rúbọ sí.Ṣé àwọn nǹkan wọnyi ni yóo mú kí inú mi yọ́?

7. Lórí òkè gíga fíofío, ni o lọ tẹ́ ibùsùn rẹ síníbẹ̀ ni o tí ń lọ rú ẹbọ.

8. O gbé ère oriṣa kalẹ̀ sí ẹ̀yìn ìlẹ̀kùn ati ẹ̀yìn òpó ìlẹ̀kùn.O kọ̀ mí sílẹ̀, o bọ́ sórí ibùsùn, o tẹ́ ibùsùn tí ó fẹ̀.O wá bá àwọn tí ó wù ọ́ da ọ̀rọ̀ pọ̀,ẹ̀ ń bá ara yín lòpọ̀.

9. O gbọ̀nà, o lọ gbé òróró fún oriṣa Moleki,o kó ọpọlọpọ turari lọ,o rán àwọn ikọ̀ lọ sí ilẹ̀ òkèèrè,o sì ranṣẹ lọ sinu isà òkú pẹlu.

10. Àárẹ̀ mú ọ nítorí ìrìn àjò rẹ jìnnà,sibẹsibẹ o kò sọ fún ara rẹ pé, “Asán ni ìrìn àjò yìí.”Ò ń wá agbára kún agbára,nítorí náà àárẹ̀ kò mú ọ.

11. Ta ni ń já ọ láyà,tí ẹ̀rù rẹ̀ bà ọ́, tí o fi purọ́;tí o kò ranti mi, tí o kò sì ronú nípa mi?Ṣé nítorí mo ti dákẹ́ fún ìgbà pípẹ́,ni o kò fi bẹ̀rù mi?

Ka pipe ipin Aisaya 57