Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 47:1-11 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Sọ̀kalẹ̀ kí o jókòó ninu eruku, ìwọ Babiloni.Jókòó ní ilẹ̀ẹ́lẹ̀, láìsí ìtẹ́-ọba,ìwọ ọmọbinrin Kalidea.A kò ní pè ọ́ ní ẹlẹgẹ́ ati aláfẹ́ mọ́.

2. Gbé ọlọ kí o máa lọ ọkà,ṣí aṣọ ìbòjú rẹ kúrò,ká aṣọ rẹ sókè, kí o ṣí ẹsẹ̀ rẹ sílẹ̀,kí o sì la odò kọjá.

3. A óo tú ọ sí ìhòòhò,a óo sì rí ìtìjú rẹ.N óo gbẹ̀san,n kò sì ní dá ẹnìkan kan sí.

4. Olùràpadà wa, tí ń jẹ́ OLUWA àwọn ọmọ ogun, ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.

5. OLUWA wí nípa Kalidea pé:“Jókòó kí o dákẹ́ jẹ́ẹ́, kí o sì wọ inú òkùnkùn lọ,ìwọ ọmọbinrin Kalidea.Nítorí a kò ní pè ọ́ ní ayaba àwọn orílẹ̀-èdè mọ́.

6. Inú bí mi sí àwọn eniyan mi,mo sì sọ nǹkan ìní mi di ohun ìríra.Mo fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́,o kò ṣàánú wọn.O di àjàgà wúwo rẹ mọ́ àwọn arúgbó lọ́rùn.

7. O sọ pé ìwọ ni o óo máa jẹ́ ayaba títí lae,nítorí náà o kò kó àwọn nǹkan wọnyi lékàn,o kò sì ranti ìgbẹ̀yìn wọn.

8. “Nítorí náà, gbọ́ nisinsinyii, ìwọ tí o fẹ́ràn afẹ́ ayé,tí o jókòó láìléwu,tí ò ń sọ lọ́kàn rẹ pé,‘Èmi nìkan ni mo wà,kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.N kò ní di opó,bẹ́ẹ̀ ni n kò ní ṣòfò ọmọ.’

9. Ọ̀fọ̀ mejeeji ni yóo ṣe ọ́ lójijì,lọ́jọ́ kan náà: o óo ṣòfò ọmọ, o óo sì di opó,ibi yìí yóo dé bá ọ lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́.Ò báà lóṣó, kí o lájẹ̀ẹ́,kí àfọ̀ṣẹ rẹ sì múná jù bẹ́ẹ̀ lọ.

10. “Ọkàn rẹ balẹ̀ ninu iṣẹ́ ibi rẹ,o ní ẹnìkan kò rí ọ.Ọgbọ́n ati ìmọ̀ rẹ mú ọ ṣìnà,ò ń sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Èmi nìkan ní mo wà.Kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.’

11. Ṣugbọn ibi yóo dé bá ọ,tí o kò ní lè dáwọ́ rẹ̀ dúró;àjálù yóo dé bá ọ,tí o kò ní lè ṣe ètùtù rẹ̀;ìparun yóo dé bá ọ lójijì,tí o kò ní mọ nǹkankan nípa rẹ̀.

Ka pipe ipin Aisaya 47