Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 43:1-8 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ṣugbọn nisinsinyii, Jakọbu,gbọ́ nǹkan tí OLUWA ẹlẹ́dàá rẹ wí,Israẹli, gbọ́ ohun tí ẹni tí ó dá ọ sọ.Ó ní, “Má bẹ̀rù, nítorí mo ti rà ọ́ pada;mo ti pè ọ́ ní orúkọ rẹ, èmi ni mo ni ọ́.

2. Nígbà tí o bá ń la ibú omi kọjá,n óo wà pẹlu rẹ;nígbà tí o bá la odò ńlá kọjá,kò ní bò ọ́ mọ́lẹ̀,nígbà tí o bá ń kọjá ninu iná, kò ní jó ọ.Ahọ́n iná kò ní jó ọ run.

3. Nítorí èmi ni OLUWA Ọlọrun rẹ,Ẹni Mímọ́ Israẹli, Olùgbàlà rẹ.Mo fi Ijipti, lélẹ̀, láti rà ọ́ pada,mo sì fi Etiopia ati Seba lélẹ̀ mo ti fi ṣe pàṣípààrọ̀ rẹ.

4. Nítorí pé o ṣọ̀wọ́n lójú mi, o níyì, mo sì fẹ́ràn rẹ,mo fi àwọn eniyan rọ́pò rẹ;mo sì fi ẹ̀mí àwọn orílẹ̀-èdè dípò ẹ̀mí rẹ.

5. Má bẹ̀rù nítorí mo wà pẹlu rẹ,n óo kó àwọn ọmọ rẹ wá láti ìlà oòrùn,n óo sì ko yín jọ láti ìwọ̀ oòrùn.

6. N óo pàṣẹ fún ìhà àríwá pé,‘Dá wọn sílẹ̀.’N óo sọ fún ìhà gúsù pé,‘O kò gbọdọ̀ dá wọn dúró.’Kó àwọn ọmọ mi ọkunrin wá láti òkèèrè,sì kó àwọn ọmọ mi obinrin wá láti òpin ayé,

7. gbogbo àwọn tí à ń fi orúkọ mi pè,àwọn tí mo dá fún ògo mi,àwọn tí mo fi ọwọ́ mi ṣẹ̀dá wọn.”

8. Ẹ mú àwọn eniyan mi jáde,àwọn tí wọ́n ní ojú, ṣugbọn tí ojú wọn ti fọ́,wọ́n ní etí, ṣugbọn etí wọn ti di.

Ka pipe ipin Aisaya 43