Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 28:10-18 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Nítorí pé gbogbo rẹ̀ tòfin-tòfin ni,èyí òfin, tọ̀hún ìlànà.Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún.”

11. Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, àwọn àjèjì tí èdè wọn yàtọ̀ ni OLUWA yóo lòláti bá àwọn eniyan wọnyi sọ̀rọ̀.

12. Àwọn tí ó ti wí fún pé:Ìsinmi nìyí,ẹ fún àwọn tí àárẹ̀ mú ní ìsinmi;ìtura nìyí.Sibẹsibẹ wọ́n kọ̀, wọn kò gbọ́.

13. Nítorí náà ọ̀rọ̀ OLUWA sí wọn yóo jẹ́ tòfin-tòfin,èyí òfin tọ̀hún ìlànà.Díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn-ún,kí wọ́n baà lè lọ ṣubú sẹ́yìnkí wọ́n sì fọ́ wẹ́wẹ́;kí á lè dẹ tàkúté sílẹ̀ fún wọn,kí ọwọ́ lè tẹ̀ wọ́n.

14. Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí,ẹ̀yin oníyẹ̀yẹ́ eniyan,tí ẹ̀ ń ṣe àkóso àwọn eniyan wọnyi ní Jerusalẹmu.

15. Nítorí ẹ wí pé:“A ti bá ikú dá majẹmu,a sì ti bá ibojì ṣe àdéhùn.Nígbà tí jamba bá ń bọ̀,kò ní dé ọ̀dọ̀ wa;nítorí a ti fi irọ́ ṣe ibi ìsádi wa,a sì ti fi èké ṣe ibi ààbò.”

16. Nítorí náà OLUWA Ọlọrun sọ pé,“Wò ó! Èmi yóo ri òkúta ìpìlẹ̀ ilé kan mọ́lẹ̀ ní Sioni,yóo jẹ́ òkúta tí ó lágbára,òkúta igun ilé iyebíye, tí ó ní ìpìlẹ̀ tí ó dájú:Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, ojú kò níí kán an.

17. Ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ni n óo fi ṣe okùn ìwọnlẹ̀,òdodo ni n óo fi ṣe ìwọ̀n ògiri.”Òjò àdàpọ̀ mọ́ yìnyín yóo gbá ibi ààbò irọ́ dànù,omi yóo sì bo ibi tí wọ́n sápamọ́ sí.

18. Majẹmu tí ẹ bá ikú dá yóo wá di òfo,àdéhùn yín pẹlu ibojì yóo sì di asán.Nígbà tí jamba bá ń ṣẹlẹ̀ káàkiri,yóo máa dé ba yín.

Ka pipe ipin Aisaya 28