Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 22:4-16 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Nítorí náà, ni mo ṣe sọ pé,“Ẹ ṣíjú kúrò lára miẹ jẹ́ kí n sọkún, kí n dami lójú pòròpòrò,ẹ má ṣòpò pé ẹ óo rẹ̀ mí lẹ́kún,nítorí ìparun àwọn ará Jerusalẹmu, àwọn eniyan mi.”

5. Nítorí OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ti ya ọjọ́ kan sọ́tọ̀,ọjọ́ ìrúkèrúdò ati ìdágìrì ati ìdàrúdàpọ̀, ní àfonífojì ìran.Ọjọ́ wíwó odi ìlú palẹ̀ati igbe kíké láàrin àwọn òkè ńlá.

6. Àwọn ọmọ ogun Elamu gbé ọfà wọn kọ́ èjìká,pẹlu kẹ̀kẹ́-ogun ati àwọn ẹlẹ́ṣin,àwọn ọmọ ogun Kiri sì tọ́jú asà wọn.

7. Àwọn àfonífojì dáradára yín kún fún kẹ̀kẹ́-ogunàwọn ẹlẹ́ṣin sì dúró sí ipò wọn lẹ́nu ibodè;

8. ó ti tú aṣọ lára Juda.Ní ọjọ́ náà, ẹ gbẹ́kẹ̀lé àwọn ohun ìjà tí ó wà ninu Ilé-Igbó,

9. ẹ rí i pé ibi tí ògiri ìlú Dafidi ti sán pọ̀, ẹ sì gbá omi inú adágún tí ó wà ní ìsàlẹ̀ jọ.

10. Ẹ ka iye ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu, ẹ sì wó àwọn kan palẹ̀ ninu wọn, kí ẹ lè rí òkúta tún odi ìlú ṣe.

11. Ẹ wa kòtò sí ààrin ògiri mejeeji, Kí ẹ lè rí ààyè fa omi inú odò àtijọ́ sí. Ṣugbọn ẹ kò wo ojú ẹni tí ó ṣe ohun tí ń ṣẹlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò bìkítà fún ẹni tí ó ṣètò rẹ̀ láti ìgbà pípẹ́ wá.

12. Ní ọjọ́ náà,OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun fi ìpè sóde pé,kí ẹ máa sọkún, kí ẹ máa ṣọ̀fọ̀,kí ẹ fá orí yín, kí ẹ sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bora.

13. Ṣugbọn dípò kí ẹ ṣe bẹ́ẹ̀,ẹ̀ ń yọ̀, inú yín ń dùn.Ẹ̀ ń pa mààlúù, ẹ̀ ń pa aguntan,ẹ̀ ń jẹ ẹran, ẹ̀ ń mu ọtí waini.Ẹ̀ ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á jẹ, kí á mu!Nítorí pé lọ́la ni a óo kú.”

14. OLUWA àwọn ọmọ ogun ti fi tó mi létí pé:“A kò ní dárí ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì yíntítí tí ẹ óo fi kú.”

15. OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ní, “Lọ bá Ṣebina, iranṣẹ ọba, tí ó jẹ́ olórí ní ààfin ọba, Kí o bi í pé:

16. ‘Kí ni o fẹ́ máa ṣe níhìn-ín? Ta ni o sì ní níhìn-ín tí o fi gbẹ́ ibojì síhìn-ín fún ara rẹ? Ìwọ tí o gbẹ́ ibojì sórí òkè, tí o kọ́ ilé fún ara rẹ ninu àpáta?

Ka pipe ipin Aisaya 22