Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 10:6-13 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Mo rán wọn láti gbógun ti àwọn tí kò mọ Ọlọrun,ati àwọn eniyan tí wọ́n bá mú mi bínú.Pé kí wọ́n kó wọn lẹ́rù.Kí wọ́n kó wọn lẹ́rúkí wọ́n tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bíi ẹrọ̀fọ̀tí à ń tẹ̀ mọ́lẹ̀ níta gbangba.

7. Ṣugbọn ọba Asiria kò pa irú ète yìí,kò sì ní irú èrò yìí lọ́kàn;gbogbo èrò ọkàn rẹ̀ ni láti pa ọpọlọpọ orílẹ̀-èdè run

8. nítorí ó wí pé:“Ṣebí ọba ni gbogbo àwọn olórí ogun mi!

9. Ṣebí bíi Kakemiṣi ni Kalino rí,tí Hamati rí bíi Aripadi,tí Samaria kò sì yàtọ̀ sí Damasku?

10. Bí ọwọ́ mi ṣe tẹ àwọn ìlú àwọn abọ̀rìṣà,tí oriṣa wọn lágbára ju ti Jerusalẹmu ati Samaria lọ,

11. ṣé n kò ní lè ṣe sí Jerusalẹmu ati àwọn oriṣa rẹ̀bí mo ti ṣe Samaria ati àwọn oriṣa rẹ̀?”

12. Nígbà tí OLUWA bá parí bírà tí ó ń dá ní òkè Sioni ati ní Jerusalẹmu,yóo fìyà jẹ ọba Asiria fún ìwà ìgbéraga ati àṣejù rẹ̀.

13. Nítorí ó ní,“Agbára mi ni mo fi ṣe èyí,ọgbọ́n mi ni mo fi ṣe énítorí pé mo jẹ́ amòye.Mo yí ààlà àwọn orílẹ̀-èdè pada,mo kó ẹrù tí ó wà ninu ilé ìṣúra wọn.Mo ré àwọn tí wọ́n jókòó lórí ìtẹ́ bọ́ sílẹ̀ bí alágbára ọkunrin.

Ka pipe ipin Aisaya 10