Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 1:17-25 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Ẹ lọ kọ́ bí eniyan tí ń ṣe rere.Ẹ máa ṣe ẹ̀tọ́.Ẹ máa ran ẹni tí ara ń ni lọ́wọ́.Ẹ máa gbìjà aláìníbaba, kí ẹ sì máa gba ẹjọ́ opó rò.”

18. OLUWA ní, “Ẹ wá ná, ẹ jẹ́ kí á jọ sọ àsọyé pọ̀.Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín tilẹ̀ pọ́n bí iná,yóo di funfun bí ẹfun.Bí ó tilẹ̀ pupa bí aṣọ àlàárì,yóo di funfun bí irun ọmọ aguntan funfun.

19. Bí ẹ bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́ràn,ẹ óo jẹ ire ilẹ̀ náà.

20. Ṣugbọn tí ẹ bá kọ̀, tí ẹ sì ṣoríkunkun;idà ni yóo run yín.”Bẹ́ẹ̀ ni OLUWA sọ.

21. Ìlú tí ó ti jẹ́ olódodo rí tí ń ṣe bí aṣẹ́wó,ìlú tí ó ti kún fún ẹ̀tọ́ ati òdodo rí, ti kún fún ìpànìyàn.

22. Fadaka rẹ ti di ìdàrọ́ mọ́ ọ lọ́wọ́.Wọ́n ti fi omi lú ọtí waini rẹ.

23. Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn ìjòyè rẹ, ati ẹgbẹ́ olè;gbogbo wọn ni wọ́n fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀,tí wọn sì ń wá ẹ̀bùn káàkiri.Wọn kì í gbèjà aláìníbaba,bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í gba ẹjọ́ opó rò.

24. Nítorí náà, OLUWA àwọn ọmọ ogun, Alágbára Israẹli ní:“N óo bínú sí àwọn ọ̀tá mi,n óo sì gbẹ̀san lára àwọn tí ó kórìíra mi.

25. Nígbà tí mo bá gbá ọ mú,n óo finá jó gbogbo àìdára rẹ dànù.N óo sì mú gbogbo ìbàjẹ́ rẹ kúrò.

Ka pipe ipin Aisaya 1