Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Títù 2:8-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. jẹ́ ẹni tó jáfáfà nínú ọ̀rọ̀ sísọ, ẹni tí kò see tanù, kí ojú kò lé tí àwọn alátakò rẹ̀ nígbà tí wón kò bá rí ohun búburú sọ nípa rẹ̀.

9. Kọ́ àwọn ẹrú láti se ìgbọ́ran sí àwọn olówó wọn nínú ohun gbogbo, láti máa gbìyànjú láti tẹ́ wọn lọ́rùn, wọn kò gbọdọ̀ gbó olówó wọn lẹ́nu,

10. wọn kò gbọdọ̀ jàwọ́n lólè ohunkóhun, ṣùgbọ́n kí wón jẹ́ ẹni tó seé gbẹ́kẹ̀lé, kí wọn ó làkàkà ní gbogbo ọ̀nà láti jẹ́ kí ìkọ́ni nípa Ọlọ́run àti Olùgbàlà ní ìtumọ̀ rere.

11. Nítorí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tó mú ìgbàlà wà ti fara hàn fún gbogbo ènìyàn.

12. Ó ń kọ́ wa láti sẹ́ àìwà-bí Ọlọ́run àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ayé, kí a gbé ìgbé ayé ìkóra-ẹni-ní-ìjánu, ìdúrósinsin àti ìwà-bí-Ọlọ́run ní ayé ìsínsìnyìí,

13. bí a ti ń wọ̀nà fún ìrètí tó ní bùkún, èyí ń ní ìfarahàn ògo Ọlọ́run wa tí ó tóbi àti Olùgbàlà wa Jésù Kírísìtì.

14. Ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún wa láti rà fún ìràpàda kúrò nínú ìwà búburú gbogbo àti kí ó sì le wẹ̀ àwọn ènìyàn kan mọ́ fún ara rẹ̀ fún iní ohun tìkara rẹ̀, àwọn tó ń ní ìtara fún iṣẹ́ rere.

15. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni kí ìwọ kí ó máa kọ wọn. Gba ni níyànjú kí ó sì máa fi gbogbo àṣẹ bániwí. Máe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó gàn ọ́.

Ka pipe ipin Títù 2