Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Títù 2:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. wọn kò gbọdọ̀ jàwọ́n lólè ohunkóhun, ṣùgbọ́n kí wón jẹ́ ẹni tó seé gbẹ́kẹ̀lé, kí wọn ó làkàkà ní gbogbo ọ̀nà láti jẹ́ kí ìkọ́ni nípa Ọlọ́run àti Olùgbàlà ní ìtumọ̀ rere.

11. Nítorí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tó mú ìgbàlà wà ti fara hàn fún gbogbo ènìyàn.

12. Ó ń kọ́ wa láti sẹ́ àìwà-bí Ọlọ́run àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ayé, kí a gbé ìgbé ayé ìkóra-ẹni-ní-ìjánu, ìdúrósinsin àti ìwà-bí-Ọlọ́run ní ayé ìsínsìnyìí,

13. bí a ti ń wọ̀nà fún ìrètí tó ní bùkún, èyí ń ní ìfarahàn ògo Ọlọ́run wa tí ó tóbi àti Olùgbàlà wa Jésù Kírísìtì.

14. Ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún wa láti rà fún ìràpàda kúrò nínú ìwà búburú gbogbo àti kí ó sì le wẹ̀ àwọn ènìyàn kan mọ́ fún ara rẹ̀ fún iní ohun tìkara rẹ̀, àwọn tó ń ní ìtara fún iṣẹ́ rere.

15. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni kí ìwọ kí ó máa kọ wọn. Gba ni níyànjú kí ó sì máa fi gbogbo àṣẹ bániwí. Máe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó gàn ọ́.

Ka pipe ipin Títù 2