Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 8:1-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nítorí náà, kò sí ìdálẹ́bi nísinsinyìí fún àwọn tí ó wà nínú Kírísitì.

2. Nítorí nípaṣẹ̀òfin ti ẹ̀mí ìyè nínú Kírísítì Jésù ti sọ mí di òmìnira kúrò lọ́wọ́ òfin ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú.

3. Nítorí ohun tí òfin kò lè ṣe, bí ó ti jẹ aláìlera nítorí ara, Ọlọ́run rán ọmọ òun tìkara rẹ̀ ní àwòrán ara ẹ̀ṣẹ̀, ó sì dá ẹ̀ṣẹ̀; àti bi ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀, ó sì dá ẹ̀ṣẹ̀ lẹ́bi nínú ara,.

4. Kí a lè mú òdodo òfin ṣẹ, nínú wa, nítorí tí àwa ve gẹ́gẹ́ bí ohun ti ara, bí kò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun ti Ẹ̀mí.

5. Àwọn tí ń ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun ti ara, wọn a máa ronú ohun ti ara; ṣùgbọ́n àwọn ti ń e gẹ́gẹ́ bí ohun ti Ẹ̀mí, wọn a máa ronú ohun ti Ẹ̀mí.

6. Ṣíṣe ìgbọ́ran sí ẹ̀mí Mímọ́ ń yọrí sí ìyè àti àlàáfíà. Ṣùgbọ́n títẹ̀lé ara ẹ̀ṣẹ̀ àtijọ́ náà ń yọrí sí ikú.

7. Nítorí pé ara ẹ̀ṣẹ̀ tí ń gbé inú wa ń tako Ọlọ́run.

8. Ìdí nì yìí tí àwọn tí ó wà lábẹ́ àkóso ara ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n sì ń tẹ̀lé ìfẹ́ ibi wọn, kò le è tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn.

9. Ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ rárá. Ara titun yín ni yóò máa se àkóso yín bí ẹ bá ń rìn nípa ẹ̀mí Ọlọ́run tí ń gbé inú yín (Ẹ rántí pé, bí ẹnìkan kò bá ní ẹ̀mí Kírísítì tí ń gbé inú rẹ̀, irú ẹni bẹ́ẹ̀ kì í se ọmọ-ẹ̀yìn Kirísítì rárá.)

10. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Kírísítì ń gbé inú yín ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀, ẹran ara yín yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀; ṣùgbọ́n ẹ̀mí mímọ́ tí ń gbé inú yín yóò fún yín ní ìyè, nítorí ó ti fún un yín ní òdodo.

11. Àti pé, bí ẹ̀mí Ọlọ́run, ẹni tí ó jí Jésù kúrò nínú òkú bá ń gbé inú yín, òun yóò mú kí ara yín tí ó kú tún wà láàyè nípa sẹ̀ ẹ̀mí mímọ́ kan náà tí ń gbé inú yín.

12. Nítorí náà ará, kò jẹ́ ọ̀rọ̀ iyàn fún un yín láti se nǹkan tí ara ẹ̀ṣẹ̀ àtijọ́ ń rọ̀ yín láti se.

13. Nítorí pé bí ẹ̀yin bá ń tẹ̀lé, ẹ̀ṣẹ̀ ti ara ẹ̀yin yóò sọnù, ẹ ó sì sègbé, ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé nípaṣẹ̀ agbára ẹ̀mí mímọ́, ẹ̀yin sẹ́gun ẹ̀mí ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ ibi rẹ̀ nínú yín, ẹ̀yin yóò yè.

14. Nítorí pé, iye àwọn tí ẹ̀mí Ọlọ́run bá ń darí ni ọmọ Ọlọ́run.

15. Àti pé, àwa kò ní láti dàbí ẹrú tó ń fi ìbẹ̀rù tẹríba fún ọ̀gá rẹ̀. Ṣùgbọ́n a ní láti hùwà bí ọmọ Ọlọ́run. Ẹni tí a sọdọmọ sí ìdílé, Ọlọ́run tó sì ń pe Ọlọ́run ní “Baba, Baba.”

Ka pipe ipin Róòmù 8