Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 3:11-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Kò sí ẹni tí òye yé,kò sí ẹni tí ó ń wá Ọlọ́run.

12. Gbogbo wọn ni ó ti yapa,wọ́n jùmọ̀ di aláìlérè;kò sí ẹni tí ń ṣe rere,kò tilẹ̀ sí ẹnìkan.”

13. “Ibojì tí ó ṣí sílẹ̀ ní Ọ̀fun wọn:ahọ́n wọn di aláìlérè; kò sí ẹni ìtànjẹ.”“Oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ lábẹ́ ètè wọn.”

14. “Ẹnu ẹni tí ó kún fún èpè àti fún oró kíkorò.”

15. “Ẹsẹ̀ wọn yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀:

16. Ìparun àti ìpọ́njú wà lọ́nà wọn.

17. Ọ̀nà àlàáfíà ni wọn kò sì mọ̀:”

18. “Ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.”

19. Àwa sì mọ̀ pé ohunkóhun tí òfin bá wí, ó ń wí fún àwọn tí ó wà lábẹ́ òfin: kí gbogbo ẹnu bá à lè dákẹ́ àti kí a lè mú gbogbo aráyé wá sábẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run.

20. Nítorí pé nípa iṣẹ́ òfin, a kì yóò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú rẹ̀: nítorí nípa òfin ni ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ti wá.

21. Ṣùgbọ́n nisinsinyìí, a ti fi òdodo Ọlọ́run hàn láìsí òfin, tí a ti ń jẹ́rí sí nípa òfin àti nípa àwọn wòlíì;

Ka pipe ipin Róòmù 3