Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 14:15-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Bí inú arakùnrin rẹ ba bàjẹ́ nítorí ohun tí ìwọ́ jẹ, ìwọ kò rìn nínú ìfẹ́ mọ́. Má se fi oúnjẹ rẹ sọ ẹni tí Kírísítì kú fún di ẹni ègbé.

16. Má se gba kí a sọ̀rọ̀ ohun tí ó gbà sí rere ní buburu.

17. Nítorí ìjọba ọ̀run kì í se jíjẹ àti mímu, bí kò se nípa ti òdodo, àlàáfíà àti ayọ̀ nínú Èmí Mímọ́,

18. nítorí ẹni tí ó bá sin Kírísítì nínú nǹkan wọ̀nyí ni ó se ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Ọlọ́run, tí ó sì ní ìyìn lọ́dọ̀ ènìyàn.

19. Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a sa gbogbo ipá wa láti máa lépa àlàáfíà, àti ohun tí àwa yóò fi gbé ara wa ró.

20. Má se dí iṣẹ́ Ọlọ́run lọ́wọ́ nítorí oúnjẹ. Gbogbo oúnjẹ ni ó mọ́, sùgbọ́n ohun búburú ni fún ẹni náà tí ó jẹ ohunkóhun tí ó le mú arákùnrin rẹ kọsẹ̀.

21. Ó sàn kí a má jẹ ẹran tàbí mu wáìnì tàbí se ohunkóhun tí yóò mú arákùnrin rẹ subú.

22. Nítorí náà, ohun tí ìwọ bá gbàgbọ́ nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí, pa á mọ́ ní àárín ìwọ àti Ọlọ́run. Alábùkún fún ni ẹni náà tí kò dá ara rẹ̀ lẹ́bi nípa ohun tí ohun gbà.

23. Ṣùgbọ́n ẹni náà tí ó se iyèméjì ni a ti dá lẹ́bi tí ó ba jẹ ẹ́, nítorí kò wá nípa ìgbàgbọ́; bẹ́ẹ̀ sì ni, ohun gbogbo tí kò bá ti ipa ìgbàgbọ́ wá, ẹ̀sẹ̀ ni.

Ka pipe ipin Róòmù 14