Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 11:31-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn wọ̀nyí tí ó ṣe àìgbọ́ràn nísinsin yìí, kí àwọn pẹ̀lú bá le rí àánú gbà nípa àánú tí a fi hàn yín.

32. Nítorí Ọlọ́run sé gbogbo wọn mọ́ pọ̀ sínú àìgbàgbọ́, kí ó le ṣàánú fún gbogbo wọn.

33. A! Ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run!Àwámáridí ìdájọ́ rẹ̀ ti rí,ọ̀nà rẹ̀ sì jù àwárí lọ!

34. “Nítorí tali ó mọ inú Olúwa?Tàbí tani íṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀?”

35. “Tàbí tani ó kọ́ fifún un,tí a kò sì san padà fún u?”

36. Nítorí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti nípa rẹ̀, àti fún un ni ohun gbogbo;ẹni tí ògo wà fún láéláé! Àmín.

Ka pipe ipin Róòmù 11