30. Nítorí gẹ̀gẹ̀ bí ẹyin kò ti gba Ọlọ́run gbọ́ rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí tí ẹ̀yin rí ànú gbà nípa àìgbàgbọ́ wọn.
31. Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn wọ̀nyí tí ó ṣe àìgbọ́ràn nísinsin yìí, kí àwọn pẹ̀lú bá le rí àánú gbà nípa àánú tí a fi hàn yín.
32. Nítorí Ọlọ́run sé gbogbo wọn mọ́ pọ̀ sínú àìgbàgbọ́, kí ó le ṣàánú fún gbogbo wọn.
33. A! Ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run!Àwámáridí ìdájọ́ rẹ̀ ti rí,ọ̀nà rẹ̀ sì jù àwárí lọ!
34. “Nítorí tali ó mọ inú Olúwa?Tàbí tani íṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀?”
35. “Tàbí tani ó kọ́ fifún un,tí a kò sì san padà fún u?”
36. Nítorí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti nípa rẹ̀, àti fún un ni ohun gbogbo;ẹni tí ògo wà fún láéláé! Àmín.