Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 6:12-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ẹ dárí gbèsè wa jì wá,Bí àwa ti ń dárí ji àwọn ajigbésè wa,

13. Ẹ má ṣe fà wá sínú ìdẹwò,Ṣùgbọ́n ẹ gbà wá lọ́wọ́ ibi.Nítorí ìjọba ni tiyín, àti agbára àti ògo, láéláé, Àmín.’

14. Nítorí náà, bí ẹ̀yin bá dárí ji àwọn tó ṣẹ̀ yín, baba yín ọ̀run náà yóò dárí jì yín.

15. Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn jì wọ́n, baba yín kò níí dárí ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.

16. “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbààwẹ̀, ẹ má ṣe fa ojú ro bí àwọn àgàbàgebè ṣe máa ń ṣe nítorí wọn máa ń fa ojú ro láti fi hàn àwọn ènìyàn pé àwọn ń gbààwẹ̀. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín wọn ti gba èrè wọn ní kíkún.

Ka pipe ipin Mátíù 6