Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 5:43-48 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

43. “Ẹ̀yin ti gbọ́ bí òfin ti wí pé, ‘Fẹ́ràn aládúgbo rẹ, kí ìwọ sì kórírà ọ̀ta rẹ̀.’

44. Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín pé, ẹ fẹ́ràn àwọn ọ̀ta yín kí ẹ sì gbàdúrà fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí yín,

45. Kí ẹ̀yin lè jẹ́ ọmọ Baba yín bi ń bẹ ní ọ̀run. Ó mú kí oòrùn rẹ̀ ràn sára ènìyàn búburú àti ènìyàn rere, ó rọ̀jò fún àwọn olódodo àti fún àwọn aláìṣòdodo.

46. Bí ẹ̀yin bá fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn yín nìkan, èrè kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn agbowó-òde kò ha ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́?

47. Àti bí ó bá sì jẹ́ pé kìkì àwọn arákùnrin yín nìkan ni ẹ̀yin ń kí, kín ni ẹ̀yin ń ṣe ju àwọn mìíràn? Àwọn abọ̀rìṣà kò ha ń ṣe bẹ́ẹ̀ bí?

48. Nítorí náà, ẹ jẹ́ pípé, gẹ́gẹ́ bí Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run ṣe jẹ́ pípé.

Ka pipe ipin Mátíù 5