Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 27:47-59 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

47. Ọ̀rọ̀ Rẹ̀ kò yé díẹ̀ nínú àwọn ẹni tí ń wòran, nígbà tíwọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, Wọ́n wí pé ọkùnrin yìí ń pe Èlíjà.

48. Lẹ́sẹ̀ kan náà, ọ̀kan nínú wọn sáré, ó mú kànrìkàn, ó tẹ̀ ẹ́ bọ inú ọtí kíkan. Ó fi lé orí ọ̀pá, ó gbé e sókè láti fi fún un mu.

49. Ṣùgbọ́n àwọn ìyókù wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀. Ẹ jẹ́ kí a wò ó bóyá Èlíjà yóò sọ̀ kalẹ̀ láti gbà á là.”

50. Nígbà tí Jésù sì kígbe ní ohùn rara lẹ́ẹ̀kan sí i, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀, ó sì kú.

51. Lójú kan náà aṣọ ìkélé tẹ̀ḿpìlì fàya, láti òkè dé ìsàlẹ̀. Ilẹ̀ sì mì tìtì. Àwọn àpáta sì sán.

52. Àwọn isà òkú sì sí sílẹ̀. Ọ̀pọ̀ àwọn olódodo ọkùnrin àti obìnrin tí ó ti kú sì tún jíǹde.

53. Wọ́n jáde wá láti isà òkú lẹ́yìn àjíǹde Jésù, wọ́n sì lọ sí ìlú mímọ́. Níbẹ̀ ni wọ́n ti fi ara han ọ̀pọ̀ ènìyàn.

54. Nígbà tí balógun ọ̀run àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n ń ṣọ Jésù rí bí ilẹ̀ ṣe mì tìtì àti ohun tí ó ṣẹlẹ̀, ẹ̀rù bà wọn gidigidi, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ ọmọ Ọlọ́run ní í sẹ!”

55. Ọ̀pọ̀ obìnrin tí ó wá láti Gálílì pẹ̀lú Jésù láti tọ́jú Rẹ̀ wọn ń wò ó láti òkèèrè.

56. Nínú àwọn obìnrin ti ó wà níbẹ̀ ni Màríà Magidalénì, àti Màríà ìyá Jákọ́bù àti Jósẹ́fù, àti ìyá àwọn ọmọ Sébédè méjèèjì wà níbẹ̀ pẹ̀lú.

57. Nígbà tí alẹ́ sì lẹ́, ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan láti Arimatíyà, tí à ń pè ní Jósẹ́fù, ọ̀kan nínú àwọn tí ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn Jésù,

58. lọ sọ́dọ̀ Pílátù, ó sì tọrọ òkú Jésù. Pílátù sì pàṣẹ kí a gbé é fún un.

59. Jósẹ́fù sì gbé òkú náà. Ó fi aṣọ funfun mímọ́ dì í.

Ka pipe ipin Mátíù 27