Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 24:30-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. “Nígbà náà ni àmì Ọmọ-Ènìyàn yóò si fi ara hàn ní ọ̀run, nígbà náà ni gbogbo ẹ̀yà ayé yóò káàánú, wọn yóò sì rí Ọmọ-Ènìyàn tí yóò máa ti ojú ọ̀run bọ̀ ti òun ti ògo àti agbára ńlá.

31. Yóò sì rán àwọn ańgẹ́lì rẹ̀ jáde pẹ̀lú ohùn ìpè ńlá, wọn yóò sì kó gbogbo àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé àti ọ̀run jọ.

32. “Nísinsìn yìí, ẹ kọ́ ẹ̀kọ́ lára igi ọ̀pọ̀tọ́: Nígbà tí ẹ̀ka rẹ̀ bá ti ń yọ titun tí ó bá sì ń ru ewé, ẹ̀yin mọ̀ pé ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn sún mọ́ tòòsí,

33. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí i tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ń ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ìpadabọ̀ mi dé tán lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.

34. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò kọjá títí tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.

35. Ọ̀run àti ayé yóò ré kọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò ré kọjá.

Ka pipe ipin Mátíù 24