Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 24:26-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. “Nítorí náà, bí ẹnìkan bá sọ fún yín pé, ‘Olùgbàlà ti dé,’ àti pé, ‘Ó wà ní ihà,’ ẹ má ṣe wàhálà láti lọ wò ó, tàbí tí wọ́n bá ní ó ń fara pamọ́ sí iyàrá, ẹ má ṣe gbà wọn gbọ́.

27. Nítorí bí mọ̀nàmọ́ná ti ń tàn láti ìlà-òòrùn títí dé ìwọ̀-oòrun, bẹ́ẹ̀ ni wíwá Ọmọ-Ènìyàn yóò jẹ́.

28. Nítorí ibikíbi tí òkú bá gbé wà, ibẹ̀ ni àwọn ẹyẹ igún ń kójọ pọ̀ sí.

29. “Lójú kan náà lẹ́yìn ìpọ́njú ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,“ ‘ni oòrùn yóò ṣókùnkùn,òṣùpá kì yóò sì fi ìmọ́lẹ̀ rẹ hàn;àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò já sílẹ̀,agbára ojú ọ̀run ni a ó mì tìtì.’

30. “Nígbà náà ni àmì Ọmọ-Ènìyàn yóò si fi ara hàn ní ọ̀run, nígbà náà ni gbogbo ẹ̀yà ayé yóò káàánú, wọn yóò sì rí Ọmọ-Ènìyàn tí yóò máa ti ojú ọ̀run bọ̀ ti òun ti ògo àti agbára ńlá.

Ka pipe ipin Mátíù 24